Orin Dafidi 55:14-17 BIBELI MIMỌ (BM)

14. À ti jọ máa sọ ọ̀rọ̀ dídùndídùn pọ̀ rí;a sì ti jọ rìn ní ìrẹ́pọ̀ ninu ilé Ọlọrun.

15. Jẹ́ kí ikú jí àwọn ọ̀tá mi pa;kí wọ́n lọ sinu isà òkú láàyè;kí wọ́n wọ ibojì lọ pẹlu ìpayà.

16. Ṣugbọn èmi ké pe Ọlọrun;OLUWA yóo sì gbà mí.

17. Mò ń ráhùn tọ̀sán-tòru,mo sì ń kérora; OLUWA óo gbọ́ ohùn mi.

Orin Dafidi 55