Orin Dafidi 51:15-19 BIBELI MIMỌ (BM)

15. OLUWA, là mí ní ohùn,n óo sì máa ròyìn iṣẹ́ ńlá rẹ.

16. Bí ó bá jẹ́ pé o fẹ́ ẹbọ ni, ǹ bá mú wá fún ọ;ṣugbọn o ò tilẹ̀ fẹ́ ẹbọ sísun.

17. Ẹbọ tí ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ ìwọ Ọlọrun ni ẹ̀mí ìròbìnújẹ́,ọkàn ìròbìnújẹ́ ati ìrònúpìwàdà ni ìwọ kì yóo gàn.

18. Jẹ́ kí ó dára fún Sioni ninu ìdùnnú rẹ;tún odi Jerusalẹmu mọ.

19. Nígbà náà ni inú rẹ yóo dùn sí ẹbọ tí ó tọ́,ẹbọ sísun, ati ẹbọ tí a sun lódidi;nígbà náà ni a óo fi akọ mààlúù rúbọ lórí pẹpẹ rẹ.

Orin Dafidi 51