Orin Dafidi 49:16-20 BIBELI MIMỌ (BM)

16. Má ba ara jẹ́ bí ẹnìkan bá di olówó,tí ọrọ̀ rẹ̀ ń pọ̀ sí i.

17. Nítorí pé ní ọjọ́ tí ó bá kú,kò ní mú ohunkohun lọ́wọ́ lọ;dúkìá rẹ̀ kò sì ní bá a wọ ibojì.

18. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nígbà tí ó wà láàyè,ó rò pé Ọlọrun bukun òun,bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé a máa yin eniyannígbà tí nǹkan bá ń dára fún un,

19. yóo kú bí àwọn baba ńlá rẹ̀ ti kú,kò sì ní fojú kan ìmọ́lẹ̀ mọ́.

20. Eniyan kò lè máa gbé inú ọlá rẹ̀ títí ayé;bí ẹranko tíí kú, ni òun náà óo ku.

Orin Dafidi 49