Orin Dafidi 44:1-2 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ọlọrun, a ti fi etí wa gbọ́,àwọn baba wa sì ti sọ fún wa,nípa àwọn ohun tí o ṣe nígbà ayé wọn,àní, ní ayé àtijọ́:

2. Ìwọ ni o fi ọwọ́ ara rẹ lé àwọn orílẹ̀-èdè jáde fún wọn,tí o sì fi ẹsẹ̀ àwọn baba wa múlẹ̀;o fi ìyà jẹ àwọn orílẹ̀-èdè náà,o sì jẹ́ kí ó dára fún àwọn baba wa.

Orin Dafidi 44