Orin Dafidi 37:32-37 BIBELI MIMỌ (BM)

32. Eniyan burúkú ń ṣọ́ olódodo,ó ń wá ọ̀nà ati pa á.

33. OLUWA kò ní fi olódodo lé e lọ́wọ́,tabi kí ó jẹ́ kí á dá olódodo lẹ́bi ní ilé ẹjọ́.

34. Gbẹ́kẹ̀lé OLUWA, sì máa tọ ọ̀nà rẹ̀,yóo gbé ọ ga, kí o lè jogún ilẹ̀ náà;nígbà tí a bá pa àwọn eniyan burúkú run, o óo fojú rẹ rí i.

35. Mo ti rí eniyan burúkú tí ń halẹ̀ mọ́ni,tí ó ga bí igi kedari ti Lẹbanoni.

36. Ṣugbọn nígbà tí mo tún gba ibẹ̀ kọjá,mo wò ó, kò sí níbẹ̀ mọ́;mo wá a, ṣugbọn n kò rí i.

37. Ṣe akiyesi ẹni pípé;sì wo olódodo dáradára,nítorí pé ìgbẹ̀yìn ẹni tí ń wá alaafia yóo dára.

Orin Dafidi 37