Orin Dafidi 20:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA óo dá ọ lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú,orúkọ Ọlọrun Jakọbu óo dáàbò bò ọ́.

2. Yóo rán olùrànlọ́wọ́ sí ọ láti ilé mímọ́ rẹ̀ wá,yóo sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.

3. Yóo ranti gbogbo ẹbọ ọrẹ rẹ,yóo sì gba ẹbọ sísun rẹ.

4. Yóo fún ọ ní ohun tí o fẹ́ ninu ọkàn rẹ,yóo sì mú gbogbo èrò rẹ ṣẹ.

5. Ìhó ayọ̀ ni a óo hó nígbà tí o bá ṣẹgun,ní orúkọ Ọlọrun wa ni a óo sì fi ọ̀págun wa sọlẹ̀;OLUWA yóo dáhùn gbogbo ìbéèrè rẹ.

Orin Dafidi 20