7. N óo kéde ohun tí OLUWA pa láṣẹ ní ti èmi ọba;Ó wí fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi,lónìí ni mo bí ọ.
8. Bèèrè lọ́wọ́ mi, èmi ó sì fún ọ ní àwọn orílẹ̀-èdè,gbogbo ayé yóo sì di tìrẹ.
9. Ìwọ óo fi ọ̀pá irin fọ́ wọn,o óo sì fọ́ wọn túútúú bí ìkòkò amọ̀.”
10. Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ kọ́gbọ́n;ẹ̀yin onídàájọ́ ayé, ẹ gba ìkìlọ̀.