Orin Dafidi 145:15-19 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Ojú gbogbo eniyan ń wò ọ́,o sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àsìkò.

16. Ìwọ la ọwọ́ rẹ,o sì tẹ́ gbogbo ẹ̀dá alààyè lọ́rùn.

17. Olódodo ni OLUWA ninu gbogbo ọ̀nà rẹ̀,aláàánú sì ni ninu gbogbo ìṣe rẹ̀.

18. OLUWA súnmọ́ gbogbo àwọn tí ń pè é,àní, àwọn tí ń pè é tọkàntọkàn.

19. Ó ń tẹ́ ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ lọ́rùn;ó ń gbọ́ igbe wọn, ó sì ń gbà wọ́n.

Orin Dafidi 145