Orin Dafidi 143:9-12 BIBELI MIMỌ (BM)

9. OLUWA, gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi;ìwọ ni mo sá di.

10. Kọ́ mi láti máa ṣe ìfẹ́ rẹ,nítorí pé ìwọ ni Ọlọrun mi.Jẹ́ kí ẹ̀mí rere rẹ máa tọ́ mi ní ọ̀nà tí ó tọ́.

11. Nítorí ti orúkọ rẹ, OLUWA, dá mi sí;ninu òtítọ́ rẹ, yọ mí ninu ìpọ́njú.

12. Ninu ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀, pa àwọn ọ̀tá mi,kí o sì pa gbogbo àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi run,nítorí pé iranṣẹ rẹ ni mí.

Orin Dafidi 143