Orin Dafidi 139:17-24 BIBELI MIMỌ (BM)

17. Ọlọrun, iyebíye ni èrò rẹ lójú mi!Wọ́n pọ̀ pupọ ní iye.

18. Bí mo bá ní kí n kà wọ́n,wọ́n pọ̀ ju iyanrìn lọ;nígbà tí mo bá sì jí,ọ̀dọ̀ rẹ náà ni n óo wà.

19. Ọlọrun, ò bá jẹ́ pa àwọn eniyan burúkú,kí àwọn apànìyàn sì kúrò lọ́dọ̀ mi.

20. Wọ́n ń sọ ọ̀rọ̀ ọ̀tẹ̀ nípa rẹ,àwọn ọ̀tá rẹ ń ba orúkọ rẹ jẹ́.

21. OLUWA, mo kórìíra àwọn tí ó kórìíra rẹ;mo sì kẹ́gàn àwọn tí ń dìtẹ̀ sí ọ?

22. Mo kórìíra wọn dé òpin;ọ̀tá ni mo kà wọ́n kún.

23. Wádìí mi, Ọlọrun, kí o mọ ọkàn mi;yẹ̀ mí wò, kí o sì mọ èrò ọkàn mi.

24. Wò ó bí ọ̀nà ibi kan bá wà tí mò ń tọ̀,kí o sì tọ́ mi sí ọ̀nà ayérayé.

Orin Dafidi 139