Orin Dafidi 138:5-8 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Wọn óo sì máa kọrin nípa iṣẹ́ OLUWA,nítorí pé ògo OLUWA tóbi.

6. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé OLUWA ga lọ́lá,ó ka àwọn onírẹ̀lẹ̀ sí,ṣugbọn ó mọ àwọn onigbeeraga lókèèrè.

7. Bí mo tilẹ̀ wà ninu ìpọ́njú,sibẹ, o dá mi sí;o dojú ìjà kọ ibinu àwọn ọ̀tá mi,o sì fi ọwọ́ agbára rẹ gbà mí.

8. OLUWA yóo mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ lórí mi,OLUWA, ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.Má kọ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ sílẹ̀.

Orin Dafidi 138