9. Jẹ́ kí àwọn alufaa rẹ wọ ẹ̀wù òdodo,kí àwọn eniyan mímọ́ rẹ sì máa kọrin ayọ̀.
10. Nítorí ti Dafidi, iranṣẹ rẹ,má jẹ́ kí ẹni tí a fi òróró rẹ yàn yíjú kúrò lára rẹ.
11. OLUWA ti ṣe ìbúra tí ó dájú fún Dafidi,èyí tí kò ní yipada; ó ní,“Ọ̀kan ninu àwọn ọmọ rẹni n óo gbé ka orí ìtẹ́ rẹ.
12. Bí àwọn ọmọ rẹ bá pa majẹmu mi mọ́,tí wọ́n sì tẹ̀lé ìlànà tí n óo fi lélẹ̀ fún wọn,àwọn ọmọ tiwọn náà óo jókòó lórí ìtẹ́ rẹ títí lae.”
13. Nítorí OLUWA ti yan Sioni;ó fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀:
14. Ó ní, “Ìhín ni ibi ìsinmi mi títí lae,níhìn-ín ni n óo máa gbé, nítorí pé ó wù mí.