Orin Dafidi 119:74-78 BIBELI MIMỌ (BM)

74. Inú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yóo máa dùnnígbà tí wọ́n bá rí mi,nítorí pé mo ní ìrètí ninu ọ̀rọ̀ rẹ.

75. OLUWA, mo mọ̀ pé ìdájọ́ rẹ tọ̀nà,ati pé lórí ẹ̀tọ́ ni o pọ́n mi lójú.

76. Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ máa tù mí ninu,gẹ́gẹ́ bí ìlérí tí o ṣe fún èmi, iranṣẹ rẹ.

77. Ṣàánú mi, kí n lè wà láàyè,nítorí pé òfin rẹ ni ìdùnnú mi.

78. Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn onigbeeraga,nítorí wọ́n ṣe àrékérekè sí mi láìnídìí;ní tèmi, n óo máa ṣe àṣàrò lórí òfin rẹ.

Orin Dafidi 119