Orin Dafidi 119:7-14 BIBELI MIMỌ (BM)

7. N óo yìn ọ́ pẹlu inú mímọ́,bí mo ṣe ń kọ́ ìlànà òdodo rẹ.

8. N óo máa pa òfin rẹ mọ́,má kọ̀ mí sílẹ̀ patapata.

9. Báwo ni ọdọmọkunrin ṣe lè mú kí ọ̀nà rẹ̀ mọ́?Nípa títẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ ni.

10. Tọkàntọkàn ni mo fi ń ṣe ìfẹ́ rẹ,má jẹ́ kí n ṣìnà kúrò ninu òfin rẹ.

11. Mo ti fi ọ̀rọ̀ rẹ sọ́kàn,kí n má baà ṣẹ̀ ọ́.

12. Ìyìn ni fún ọ, OLUWA,kọ́ mi ní ìlànà rẹ!

13. Mo fi ẹnu mi kéde gbogbo àṣẹ tí o pa.

14. Mo láyọ̀ ninu pípa òfin rẹ mọ́,bí ẹni tí ó ní ọpọlọpọ ọrọ̀.

Orin Dafidi 119