Orin Dafidi 119:169-174 BIBELI MIMỌ (BM)

169. Jẹ́ kí igbe mi dé ọ̀dọ̀ rẹ, OLUWA,fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

170. Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi dé iwájú rẹ,kí o sì gbà mí là gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

171. Ẹnu mi yóo kún fún ìyìn rẹ,pé o ti kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

172. N óo máa fi ọ̀rọ̀ rẹ ṣe orin kọ,nítorí pé gbogbo òfin rẹ ni ó tọ̀nà.

173. Múra láti ràn mí lọ́wọ́,nítorí pé mo ti gba ẹ̀kọ́ rẹ.

174. Ọkàn mi ń fà sí ìgbàlà rẹ, OLUWA;òfin rẹ sì ni inú dídùn mi.

Orin Dafidi 119