Orin Dafidi 119:151-160 BIBELI MIMỌ (BM)

151. Ṣugbọn ìwọ wà nítòsí, OLUWA,òtítọ́ sì ni gbogbo òfin rẹ.

152. Ó pẹ́ tí mo ti kọ́ ninu ìlànà rẹ,pé o ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí lae.

153. Wo ìpọ́njú mi, kí o gbà mí,nítorí n kò gbàgbé òfin rẹ.

154. Gba ẹjọ́ mi rò, kí o sì gbà mí,sọ mí di alààyè gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

155. Ìgbàlà jìnnà sí àwọn eniyan burúkú,nítorí wọn kò wá ìlànà rẹ.

156. Àánú rẹ pọ̀, OLUWA,sọ mí di alààyè gẹ́gẹ́ bí òtítọ́ rẹ.

157. Àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi ati àwọn ọ̀tá mi pọ̀,ṣugbọn n kò yapa kúrò ninu ìlànà rẹ.

158. Mò ń wo àwọn ọ̀dàlẹ̀ pẹlu ìríra,nítorí wọn kì í pa òfin rẹ mọ́.

159. Wo bí mo ti fẹ́ ẹ̀kọ́ rẹ tó!Dá mi sí gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

160. Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ,gbogbo òfin òdodo rẹ ni yóo máa wà títí lae.

Orin Dafidi 119