Orin Dafidi 119:12-21 BIBELI MIMỌ (BM)

12. Ìyìn ni fún ọ, OLUWA,kọ́ mi ní ìlànà rẹ!

13. Mo fi ẹnu mi kéde gbogbo àṣẹ tí o pa.

14. Mo láyọ̀ ninu pípa òfin rẹ mọ́,bí ẹni tí ó ní ọpọlọpọ ọrọ̀.

15. N óo máa ṣe àṣàrò ninu òfin rẹ,n óo sì kọjú sí ọ̀nà rẹ.

16. N óo láyọ̀ ninu àwọn ìlànà rẹ,n kò ní gbàgbé ọ̀rọ̀ rẹ.

17. Ṣe ọpọlọpọ oore fún èmi iranṣẹ rẹ,kí n lè wà láàyè,kí n sì máa tẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.

18. Là mí lójú, kí n lè rí àwọn nǹkan ìyanutí ó wà ninu òfin rẹ.

19. Àlejò ni mí láyé,má fi òfin rẹ pamọ́ fún mi.

20. Òùngbẹ títẹ̀lé òfin rẹ ń gbẹ ọkàn mi, nígbà gbogbo.

21. O bá àwọn onigbeeraga wí, àwọn ẹni ègún,tí wọn kò pa òfin rẹ mọ́.

Orin Dafidi 119