Orin Dafidi 113:3-8 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Láti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ oòrùn,kí á máa yin orúkọ OLUWA.

4. OLUWA ju gbogbo orílẹ̀-èdè lọ,ògo rẹ̀ sì ga ju ọ̀run lọ.

5. Ta ló dàbí OLUWA Ọlọrun wa,tí ó gúnwà sí òkè ọ̀run,

6. ẹni tí ó bojú wo ilẹ̀láti wo ọ̀run ati ayé?

7. Ó gbé talaka dìde láti inú erùpẹ̀,ó sì gbé aláìní sókè láti orí eérú,

8. láti mú wọn jókòó láàrin àwọn ìjòyè,àní, àwọn ìjòyè àwọn eniyan rẹ̀.

Orin Dafidi 113