Orin Dafidi 106:2-8 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Ta ló lè sọ iṣẹ́ agbára OLUWA tán?Ta ló sì lè fi gbogbo ìyìn rẹ̀ hàn?

3. Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ń ṣe ẹ̀tọ́,àwọn tí ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà nígbà gbogbo.

4. Ranti mi, OLUWA, nígbà tí o bá ńṣí ojurere wo àwọn eniyan rẹ.Ràn mí lọ́wọ́ nígbà tí o bá ń gbà wọ́n là.

5. Kí n lè rí ire àwọn àyànfẹ́ rẹkí n lè ní ìpín ninu ayọ̀ àwọn eniyan rẹ,kí n sì lè máa ṣògo pẹlu àwọn tí ó jẹ́ eniyan ìní rẹ.

6. A ti ṣẹ̀, àtàwa, àtàwọn baba wa,a ti ṣe àìdára, a sì ti hùwà burúkú.

7. Nígbà tí àwọn baba ńlá wa wà ní Ijipti,wọn kò náání iṣẹ́ ìyanu rẹ,wọn kò sì ranti bí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ti pọ̀ tó.Ṣugbọn wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá Ògo lẹ́bàá òkun pupa.

8. Sibẹsibẹ, ó gbà wọ́n là, nítorí orúkọ rẹ̀;kí ó lè fi títóbi agbára rẹ̀ hàn.

Orin Dafidi 106