Orin Dafidi 104:30-35 BIBELI MIMỌ (BM)

30. Nígbà tí o rán ẹ̀mí rẹ jáde,wọ́n di ẹ̀dá alààyè,o sì sọ orí ilẹ̀ di ọ̀tun.

31. Kí ògo OLUWA máa wà títí lae,kí OLUWA máa yọ̀ ninu iṣẹ́ rẹ̀.

32. Ẹni tí ó wo ilẹ̀, tí ilẹ̀ mì tìtì,tí ó fọwọ́ kan òkè, tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí yọ èéfín.

33. N óo kọrin ìyìn sí OLUWAníwọ̀n ìgbà tí mo bá wà láàyè.N óo máa kọrin ìyìn sí Ọlọrun mi,níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀mí mi bá ń bẹ.

34. Kí àṣàrò ọkàn mi kí ó dùn mọ́ ọn ninunítorí mo láyọ̀ ninu OLUWA.

35. Kí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ parẹ́ lórí ilẹ̀ ayé,kí àwọn eniyan burúkú má sí mọ́.Yin OLUWA, ìwọ ọkàn mi!Yin OLUWA!

Orin Dafidi 104