Orin Dafidi 103:7-15 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Ó fi ọ̀nà rẹ̀ han Mose,ó sì ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ han àwọn ọmọ Israẹli.

8. Aláàánú ati olóore ni OLUWA,kì í tètè bínú, ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ sì pọ̀.

9. Kì í fi ìgbà gbogbo báni wí,bẹ́ẹ̀ ni ibinu rẹ̀ kì í pẹ́ títí ayé.

10. Kì í ṣe sí wa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ wa,bẹ́ẹ̀ ni kì í san án fún wa bí àìdára wa.

11. Nítorí bí ọ̀run ti jìnnà sí ilẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ ṣe tóbi tósí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.

12. Bí ìlà oòrùn ti jìnnà sí ìwọ oòrùn,bẹ́ẹ̀ ni ó mú ẹ̀ṣẹ̀ wa jìnnà sí wa.

13. Bí baba ti máa ń ṣàánú àwọn ọmọ rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni OLUWA máa ń ṣàánú àwọntí ó bá bẹ̀rù rẹ̀.

14. Nítorí ó mọ ẹ̀dá wa;ó ranti pé erùpẹ̀ ni wá.

15. Ọjọ́ ayé ọmọ eniyan dàbí ti koríko,eniyan a sì máa gbilẹ̀ bí òdòdó inú igbó;

Orin Dafidi 103