4. ẹni tí ó ń yọ ẹ̀mí rẹ kúrò ninu ọ̀fìn,tí ó fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ ati àánú dé ọ ládé.
5. Ẹni tí ó ń fi ohun dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn,tí ó fi ń sọ agbára ìgbà èwe rẹ dọ̀tun bíi ti idì.
6. OLUWA a máa dáni lárea sì máa ṣe ìdájọ́ òdodo fún gbogboàwọn tí a ni lára.
7. Ó fi ọ̀nà rẹ̀ han Mose,ó sì ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ han àwọn ọmọ Israẹli.