Orin Dafidi 102:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Gbọ́ adura mi, OLUWA;kí o sì jẹ́ kí igbe mi dé ọ̀dọ̀ rẹ.

2. Má yọwọ́ lọ́ràn mi lọ́jọ́ ìṣòro!Dẹtí sí adura mi;kí o sì tètè dá mi lóhùn nígbà tí mo bá ké pè ọ́.

3. Nítorí ọjọ́ ayé mi ń kọjá lọ bí èéfín,eegun mi gbóná bí iná ààrò.

4. Ìdààmú bá ọkàn mi, mo rọ bíi koríko,tóbẹ́ẹ̀ tí mo gbàgbé láti jẹun.

Orin Dafidi 102