Orin Dafidi 10:9-12 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Ó fara pamọ́ bíi kinniun tí ó wà ní ibùba;ó fara pamọ́ láti ki aláìní mọ́lẹ̀;ó mú aláìní, ó sì fi àwọ̀n fà á lọ.

10. Ó wó aláìṣẹ̀ mọ́lẹ̀, ó tẹ orí wọn ba,ó sì fi agbára bì wọ́n ṣubú.

11. Ó sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé, “Ọlọrun ti gbàgbé,OLUWA ti gbé ojú kúrò, kò sì ní rí i laelae.”

12. Dìde, OLUWA; Ọlọrun, wá nǹkankan ṣe sí i;má sì gbàgbé àwọn tí a nilára.

Orin Dafidi 10