Nọmba 31:10-14 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Wọ́n fi iná sun gbogbo ìlú wọn ati àwọn abúlé wọn,

11. wọ́n kó gbogbo ìkógun: eniyan ati ẹranko.

12. Wọ́n kó wọn wá sọ́dọ̀ Mose ati Eleasari ati gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, ní òdìkejì odò Jọdani, lẹ́bàá Jẹriko.

13. Mose, Eleasari ati àwọn olórí jáde lọ pàdé àwọn ọmọ ogun náà lẹ́yìn ibùdó.

14. Mose bínú sí àwọn olórí ogun náà ati sí olórí ẹgbẹẹgbẹrun ati olórí ọgọọgọrun-un.

Nọmba 31