17. OLUWA sọ fún Mose pé, “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé,
18. Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mò ń mu yín lọ,
19. tí ẹ bá jẹ ninu oúnjẹ ilẹ̀ náà, ẹ óo mú ọrẹ wá fún OLUWA.
20. Ẹ mú ọrẹ wá fún OLUWA lára àwọn àkàrà tí ẹ kọ́kọ́ ṣe gẹ́gẹ́ bí ọrẹ láti ibi ìpakà.
21. Lára àwọn àkàrà tí ẹ bá kọ́kọ́ ṣe ni ẹ óo máa mú wá fi ṣe ọrẹ fún OLUWA ní ìrandíran yín.