Nahumu 1:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ọ̀rọ̀ OLUWA nìyí; tí a kọ sinu ìwé ìran tí Nahumu ará Elikoṣi rí nípa ìlú Ninefe.

2. OLUWA tíí jowú tíí sìí máa gbẹ̀san ni Ọlọrun.OLUWA a máa gbẹ̀san, a sì máa bínú.OLUWA a máa gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀,a sì máa fi ìrúnú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ọ̀tá rẹ̀.

3. OLUWA kì í tètè bínú;ó lágbára lọpọlọpọ,kì í sìí dá ẹni tí ó bá jẹ̀bi láre.Ipa ọ̀nà rẹ̀ wà ninu ìjì ati ẹ̀fúùfù líle,awọsanma sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.

4. Ó bá òkun wí, ó mú kí ó gbẹ,ó sì mú kí gbogbo odò gbẹ pẹlu;koríko ilẹ̀ Baṣani ati ti òkè Kamẹli gbẹ,òdòdó ilẹ̀ Lẹbanoni sì rẹ̀.

Nahumu 1