Kronika Kinni 17:24-27 BIBELI MIMỌ (BM)

24. Orúkọ rẹ yóo fìdí múlẹ̀ sí i, àwọn eniyan rẹ yóo sì máa gbé ọ́ ga títí lae, wọn yóo máa wí pé ‘OLUWA àwọn ọmọ ogun, tí ó jẹ́ Ọlọrun Israẹli ni Israẹli mọ̀ ní Ọlọrun,’ ati pé ìdílé Dafidi, iranṣẹ rẹ, yóo fìdí múlẹ̀ sí i níwájú rẹ.

25. Nítorí pé ìwọ Ọlọrun mi, ti fi han èmi iranṣẹ rẹ pé o óo fìdí ìdílé mi múlẹ̀, nítorí náà ni mo ṣe ní ìgboyà láti gbadura sí ọ.

26. OLUWA, ìwọ ni Ọlọrun, o ti ṣe ìlérí ohun rere yìí fún èmi iranṣẹ rẹ.

27. Nítorí náà, jẹ́ kí ó wù ọ́ láti bukun ìdílé èmi iranṣẹ rẹ, kí ìdílé mi lè wà níwájú rẹ títí lae, nítorí ẹnikẹ́ni tí o bá bukun, olúwarẹ̀ di ẹni ibukun títí lae.”

Kronika Kinni 17