1. Ní ọjọ́ kan ní àkókò tí Dafidi ọba ń gbe ààfin rẹ̀, ó sọ fún Natani, wolii, pé, “Wò ó, èmi ń gbé ilé tí a fi igi kedari kọ́, ṣugbọn Àpótí Majẹmu OLUWA wà ninu àgọ́.”
2. Natani bá dá a lóhùn pé, “Ṣe gbogbo nǹkan tí ó wà lọ́kàn rẹ, nítorí pé Ọlọrun wà pẹlu rẹ.”
3. Ṣugbọn ní alẹ́ ọjọ́ náà gan-an, Ọlọrun sọ fún Natani pé,