Kronika Kinni 16:10-16 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Ẹ máa fi orúkọ rẹ̀ ṣògo,kí ọkàn àwọn tí wọn ń sin OLUWA kún fún ayọ̀.

11. OLUWA ni kí ẹ máa tọ̀ lọ fún ìrànlọ́wọ́,Ẹ máa sìn ín nígbà gbogbo.

12. Ẹ ranti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀,gbogbo nǹkan ìyanu tí ó ṣe, ati gbogbo ìdájọ́ rẹ̀,

13. ẹ̀yin ọmọ Abrahamu, iranṣẹ rẹ̀,ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.

14. Òun ni OLUWA Ọlọrun wa,ìdájọ́ rẹ̀ ká gbogbo ayé.

15. Kò ní í gbàgbé majẹmu rẹ̀ títí lae,àní àwọn ohun tí ó ti pa láṣẹ láti ṣe fún ẹgbẹẹgbẹrun ìran,

16. majẹmu tí ó bá Abrahamu dá,ìlérí tí ó ti ṣe fún Isaaki,

Kronika Kinni 16