Kronika Kinni 1:19-29 BIBELI MIMỌ (BM)

19. Eberi bí ọmọkunrin meji: Ekinni ń jẹ́ Pelegi, (nítorí pé ní àkókò tirẹ̀ ni àwọn eniyan ayé pín sí meji); ọmọ Eberi keji sì ń jẹ́ Jokitani,

20. Jokitani ni ó bí Alimodadi, Ṣelefu, Hasarimafeti, ati Jera;

21. Hadoramu, Usali, ati Dikila;

22. Ebali, Abimaeli, ati Ṣeba,

23. Ofiri, Hafila ati Jobabu; Àwọn ni àwọn ọmọ Jokitani.

24. Arọmọdọmọ Ṣemu títí fi dé orí Abramu nìyí: Ṣemu, Apakiṣadi, Ṣela;

25. Eberi, Pelegi, Reu;

26. Serugi, Nahori, Tẹra;

27. Abramu, tí a tún ń pè ní Abrahamu.

28. Àwọn ọmọ Abrahamu ni Isaaki ati Iṣimaeli.

29. Àkọsílẹ̀ ìran wọn nìyí: Nebaiotu ni àkọ́bí Iṣimaeli, lẹ́yìn náà ni ó bí Kedari, Adibeeli, ati Mibisamu;

Kronika Kinni 1