Johanu 4:15-20 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Obinrin náà sọ fún un pé, “Alàgbà, fún mi ní omi yìí kí òùngbẹ má baà gbẹ mí mọ́, kí n má baà tún wá pọn omi níhìn-ín mọ́.”

16. Jesu wí fún un pé, “Lọ pe ọkọ rẹ wá ná.”

17. Obinrin náà dáhùn pé, “Èmi kò ní ọkọ.”Jesu wí fún un pé, “O wí ire pé o kò ní ọkọ,

18. nítorí o ti ní ọkọ marun-un rí, ẹni tí o wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nisinsinyii kì í sì í ṣe ọkọ rẹ. Òtítọ́ ni o sọ.”

19. Obinrin náà sọ fún un pé, “Alàgbà, mo wòye pé wolii ni ọ́.

20. Ní orí òkè tí ó wà lọ́hùn-ún yìí ni àwọn baba wa ń sin Ọlọrun, ṣugbọn ẹ̀yin wí pé Jerusalẹmu ni ibi tí a níláti máa sìn ín.”

Johanu 4