Johanu 12:10-15 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Àwọn olórí alufaa bá pinnu láti pa Lasaru,

11. nítorí pé nítorí rẹ̀ ni ọpọlọpọ àwọn Juu ṣe ń kúrò ninu ẹ̀sìn wọn, tí wọn ń gba Jesu gbọ́.

12. Ní ọjọ́ keji, ọpọlọpọ eniyan tí ó wá ṣe àjọ̀dún gbọ́ pé Jesu ń bọ̀ wá sí Jerusalẹmu.

13. Wọ́n bá mú imọ̀ ọ̀pẹ, wọ́n jáde lọ pàdé rẹ̀, wọ́n ń kígbe pé, “Hosana! Olùbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ ní orúkọ Oluwa ati ọba Israẹli.”

14. Jesu rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, ó bá gùn un, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé,

15. “Má bẹ̀rù mọ́, ọdọmọbinrin Sioni,Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá,ó gun ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.”

Johanu 12