Jobu 39:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. “Ǹjẹ́ o mọ ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ?Ṣé o ti ká àgbọ̀nrín mọ́ ibi tí ó ti ń bímọ rí?

2. Ǹjẹ́ o lè ka iye oṣù tí wọ́n fi ń lóyún?Tabi o mọ ìgbà tí wọ́n bímọ?

3. Ǹjẹ́ o mọ ìgbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀,tí wọ́n sì bímọ?

4. Àwọn ọmọ wọn á di alágbára,wọn á dàgbà ninu pápá,wọn á sì lọ, láìpadà wá sọ́dọ̀ àwọn òbí wọn mọ́.

5. “Ta ló fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ lómìniratí ó sì tú ìdè rẹ̀?

6. Mo fi inú pápá ṣe ilé rẹ̀,ilẹ̀ oníyọ̀ sì di ibùgbé rẹ̀.

Jobu 39