Jobu 36:30-33 BIBELI MIMỌ (BM)

30. Ó fi mànàmáná yí ara rẹ̀ ká,ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.

31. Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe ń ṣàkóso àwọn orílẹ̀-èdè;ó sì ń fún wọn ní oúnjẹ lọpọlọpọ.

32. Ìkáwọ́ rẹ̀ ni mànàmáná wà,ó sì ń rán ààrá láti sán lu ohun tí ó bá fẹ́.

33. Ìró ààrá ń kéde bíbọ̀ rẹ̀,àwọn ẹran ọ̀sìn sì mọ̀ pé ó súnmọ́ tòsí.

Jobu 36