Jobu 24:4-9 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Wọn a ti àwọn aláìní kúrò lójú ọ̀nà,gbogbo àwọn talaka a sì lọ sápamọ́.

5. “Àwọn aláìní a máa ṣe làálàá káàkiri,bíi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ inú aṣálẹ̀,wọn a máa wá oúnjẹ fún àwọn ọmọ wọn ninu aṣálẹ̀.

6. Wọn a máa kó oúnjẹ jọ fún ẹran wọn ninu oko olókowọn a sì máa he èso àjàrà ní oko ìkà.

7. Wọn a máa sùn ní ìhòòhò ní gbogbo òru,wọn kìí sìí rí aṣọ fi bora nígbà òtútù.

8. Òjò a pa wọ́n lórí òkè,wọn a máa rọ̀ mọ́ àpáta nítorí àìsí ààbò.

9. (Àwọn kan ń já àwọn ọmọ aláìníbaba gbà lẹ́nu ọmú,wọ́n sì ń gba ọmọ ọwọ́ lọ́wọ́ àwọn aláìní gẹ́gẹ́ bí ohun ìdógò.)

Jobu 24