Jobu 21:4-9 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Ṣé eniyan ni mò ń bá rojọ́ ni?Kí ló dé tí n óo fi mú sùúrù?

5. Ẹ wò mí, kí ẹnu yà yín,kí ẹ sì fọwọ́ bo ẹnu.

6. Nígbà tí mo ro ohun tí ó dé bá mi,ẹ̀rù bà mí, mo sì wárìrì.

7. Kí ló dé tí eniyan burúkú fi wà láàyè,tí ó di arúgbó, tí ó sì di alágbára?

8. Àwọn ọmọ wọn ati arọmọdọmọ wọndi eniyan pataki pataki lójú ayé wọn.

9. Kò sí ìfòyà ninu ilé wọn,bẹ́ẹ̀ ni Ọlọrun kò jẹ wọ́n níyà.

Jobu 21