Jobu 19:6-12 BIBELI MIMỌ (BM)

6. ẹ mọ̀ dájú pé Ọlọrun ni ó dá mi lẹ́bi,tí ó sì fi àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.

7. Mò ń kérora pé wọ́n dá mi lóró,ṣugbọn kò sí ẹni tí ó dá mi lóhùn;mo pariwo, pariwo,ṣugbọn kò sí ẹni tí ó dìde láti ṣe ẹ̀tọ́.

8. Ọlọrun ti dí ọ̀nà mọ́ mi, kí n má baà kọjá,ó mú ọ̀nà mi ṣókùnkùn.

9. Ó bọ́ ògo mi kúrò,ó sì gba adé orí mi.

10. Ó ba ayé mi jẹ́ ní gbogbo ọ̀nà,ó sì ti parí fún mi,ó fa ìrètí mi tu bí ẹni fa igi tu.

11. Ibinu rẹ̀ ń jó mi bí iná,ó kà mí kún ọ̀tá rẹ̀.

12. Àwọn ọmọ ogun rẹ̀ kó ara wọn jọ,wọ́n dó tì mí,wọ́n sì pa àgọ́ tiwọn yí àgọ́ mi ká.

Jobu 19