Jobu 18:10-16 BIBELI MIMỌ (BM)

10. A dẹ okùn sílẹ̀ fún un,a sì dẹ pańpẹ́ sí ojú ọ̀nà rẹ̀.

11. “Ìbẹ̀rù yí i ká,wọ́n ń lé e kiri.

12. Ebi pa agbára mọ́ ọn ninu,ìṣòro sì ti ṣetán láti gbé e ṣubú.

13. Àìsàn burúkú jẹ awọ ara rẹ̀,àkọ́bí ikú jẹ ẹ́ tọwọ́ tẹsẹ̀.

14. A fipá wọ́ ọ kúrò ninu àgọ́ rẹ̀ tí ó gbẹ́kẹ̀lé,a sì mú un lọ sọ́dọ̀ Ọba Ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀.

15. Àgọ́ rẹ̀ kún fún àwọn tí kì í ṣe tirẹ̀,imí-ọjọ́ fọ́nká sí gbogbo ibùgbé rẹ̀.

16. Gbòǹgbò rẹ̀ gbẹ nísàlẹ̀,ẹ̀ka rẹ̀ sì gbẹ lókè.

Jobu 18