Jobu 15:4-8 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Ṣugbọn ò ń kọ ìbẹ̀rù Ọlọrun sílẹ̀,o sì ń dènà adura níwájú rẹ̀.

5. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni ó ń fa irú ọ̀rọ̀ tí ń ti ẹnu rẹ jáde,ètè rẹ sì kún fún àrékérekè.

6. Ẹnu rẹ ni ó dá ọ lẹ́bi, kì í ṣe èmi;ẹ̀rí tí ò ń jẹ́ nípa rẹ ní ń ta kò ọ́.

7. “Ṣé ìwọ ni ẹni kinni tí wọ́n kọ́ bí láyé?Tabi o ṣàgbà àwọn òkè?

8. Ṣé o wà ninu ìgbìmọ̀ Ọlọrun?Tabi ìwọ nìkan ni o rò pé o gbọ́n?

Jobu 15