Jobu 15:21-27 BIBELI MIMỌ (BM)

21. Etí rẹ̀ kún fún igbe tí ó bani lẹ́rù,ninu ìdẹ̀ra rẹ̀ àwọn apanirun yóo dìde sí i.

22. Kò gbàgbọ́ pé òun lè jáde kúrò ninu òkùnkùn;ati pé dájú, ikú idà ni yóo pa òun.

23. Ó ń wá oúnjẹ káàkiri, ó ń bèèrè pé,‘Níbo ló wà?’Òun gan-an sì nìyí, oúnjẹ àwọn igún!Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn ti súnmọ́ tòsí.

24. Ìdààmú ati ìrora dẹ́rùbà á,wọ́n ṣẹgun rẹ̀, bí ọba tí ó múra ogun.

25. Nítorí pé ó ṣíwọ́ sókè sí Ọlọrun,o sì ṣe oríkunkun sí Olodumare,

26. ó ń ṣe oríkunkun sí i,ó sì gbé apata tí ó nípọn lọ́wọ́ láti bá a jà;

27. nítorí pé ó sanra tóbẹ́ẹ̀ tí ojú rẹ̀ yíbò,ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ sì jẹ́ kìkì ọ̀rá.

Jobu 15