Jobu 10:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. “Ayé sú mi,nítorí náà n kò ní dákẹ́ ìráhùn;n óo sọ̀rọ̀ pẹlu ìbànújẹ́ ọkàn.

2. N óo sọ fún Ọlọrun pékí ó má dá mi lẹ́bi;kí ó sì jẹ́ kí n mọ ìdítí ó fi ń bá mi jà.

3. Ṣé ohun tí ó dára ni, Ọlọrunpé kí o máa ni eniyan lára,kí o kórìíra iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,kí o sì fẹ́ràn ète ẹni ibi?

4. Ǹjẹ́ ojú rẹ dàbí ti eniyan?Ǹjẹ́ a máa rí nǹkan bí eniyan ṣe rí i?

5. Ǹjẹ́ bí ọjọ́ ti eniyan ni ọjọ́ rẹ rí?Ǹjẹ́ ọdún rẹ rí bíi ti eniyan?

Jobu 10