Jeremaya 5:7-10 BIBELI MIMỌ (BM)

7. OLUWA bi Israẹli pé,“Báwo ni mo ṣe lè dárí ẹ̀ṣẹ̀ jìn ọ́?Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀,wọ́n sì ti ń fi àwọn ohun tí kì í ṣe ọlọrun búra.Nígbà tí mo bọ́ wọn ní àbọ́yó tán,wọ́n ṣe àgbèrè,wọ́n dà lọ sí ilé àwọn alágbèrè.

8. Wọ́n dàbí akọ ẹṣin tí a kò tẹ̀ lọ́dàá, tí ó yó,olukuluku wọn ń lé aya aládùúgbò rẹ̀ kiri.

9. Ṣé n kò wá ní jẹ wọ́n níyà fún àwọn nǹkan tí wọ́n ṣe wọnyi?Àbí n kò ní gbẹ̀san ara mi lára irú orílẹ̀-èdè yìí?

10. Kọjá lọ láàrin ọgbà àjàrà rẹ̀ ní poro ní poro, kí o sì pa á run,ṣugbọn má ṣe pa gbogbo rẹ̀ run tán.Gé àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kúrò,nítorí pé wọn kì í ṣe ti OLUWA.

Jeremaya 5