Jeremaya 4:17-23 BIBELI MIMỌ (BM)

17. Wọ́n yí i ká bí àwọn tí ó ń ṣọ́ oko,nítorí pé ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí OLUWA.OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.

18. Ìrìn ẹsẹ̀ rẹ ati ìwà rẹni ó mú kí àwọn nǹkan wọnyi dé bá ọ.Ìjìyà rẹ nìyí, ó sì korò;ó ti dé oókan àyà rẹ.

19. Oró ò! Oró ò!Mò ń jẹ̀rora!Àyà mi ò!Àyà mi ń lù kìkìkì,n kò sì lè dákẹ́;nítorí mo gbọ́ ìró fèrè ogun, ati ariwo ogun.

20. Àjálù ń ṣubú lu àjálù,gbogbo ilẹ̀ ti parun.Lójijì àgọ́ mi wó lulẹ̀,aṣọ títa mi sì fàya ní ìṣẹ́jú kan.

21. Yóo ti pẹ́ tó tí n óo máa wo àsíá ogun,tí n óo sì máa gbọ́ fèrè ogun?

22. OLUWA ní, “Nítorí pé àwọn eniyan mi gọ̀,wọn kò mọ̀ mí.Òmùgọ̀ ọmọ ni wọ́n;wọn kò ní òye.Ọgbọ́n àtiṣe ibi kún inú wọn:ṣugbọn wọn kò mọ rere ṣe.”

23. Mo bojú wo ilé ayé, ilé ayé ṣófo,ó rí júujùu;mo ṣíjú wo ojú ọ̀run,kò sí ìmọ́lẹ̀ níbẹ̀.

Jeremaya 4