7. “Nítorí náà àkókò kan ń bọ̀, tí wọn kò ní máa búra ní orúkọ OLUWA tí ó kó àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ijipti mọ́,
8. ṣugbọn tí wọn yóo máa wí pé, ‘Ní orúkọ OLUWA tí ó kó àwọn ọmọ ilé Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá, ati gbogbo ilẹ̀ tí wọn kó wọn lẹ́rú lọ, tí ó sì mú wọn pada sí ilẹ̀ wọn.’ Wọn óo wá máa gbé orí ilẹ̀ wọn nígbà náà. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”
9. Ọkàn mi bàjẹ́ nítorí àwọn wolii,gbogbo ara mi ń gbọ̀n.Mo dàbí ọ̀mùtí tí ó ti mu ọtí yó,mo dàbí ẹni tí ọtí ń pa,nítorí OLUWA, ati nítorí ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
10. Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún àgbèrè ẹ̀sìn,ọ̀nà ibi ni wọ́n ń tọ̀,wọn kò sì lo agbára wọn ní ọ̀nà ẹ̀tọ́nítorí ègún, ilẹ̀ ti di gbígbẹgbogbo pápá oko ló ti gbẹ.
11. Ati wolii, ati alufaa, ìwà burúkú ni wọ́n ń hù,ní ilé mi pàápàá mo rí iṣẹ́ ibi wọn,èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.