Jeremaya 18:12-15 BIBELI MIMỌ (BM)

12. Ṣugbọn wọ́n ń wí pé, ‘Rárá o, OLUWA kàn ń sọ tirẹ̀ ni, tinú wa ni a óo ṣe, olukuluku yóo máa lo agídí ọkàn rẹ̀.’ ”

13. Nítorí náà OLUWA ní,“Ẹ bèèrè láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè,bí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ irú rẹ̀ rí.Israẹli ti ṣe ohun tó burú gan-an.

14. Ṣé yìnyín òkè Lẹbanoni a máa dà ní pàlàpálá Sirioni?Àbí omi tútù tí máa ń ṣàn láti inú òkè rẹ̀ a máa gbẹ?

15. Ṣugbọn àwọn eniyan mi ti gbàgbé mi,wọ́n ń sun turari sí oriṣa èké.Wọ́n ti kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà àtijọ́ tí wọn ń tọ̀,wọ́n ti yà sí ọ̀nà ojúgbó tí kì í ṣe ojú ọ̀nà tààrà.

Jeremaya 18