Jẹnẹsisi 6:20-22 BIBELI MIMỌ (BM)

20. Meji meji yóo tọ̀ ọ́ wá ninu oríṣìíríṣìí àwọn ẹyẹ, ati oríṣìíríṣìí àwọn ẹran ọ̀sìn, ati oríṣìíríṣìí àwọn ohun tí ń fàyà fà lórí ilẹ̀, kí o lè mú kí wọ́n wà láàyè pẹlu rẹ.

21. Kí o sì kó oniruuru oúnjẹ sinu ọkọ̀ náà fún ara rẹ ati fún wọn.”

22. Noa bá ṣe gbogbo ohun tí Ọlọrun pàṣẹ fún un.

Jẹnẹsisi 6