Ìwé Òwe 7:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́,kí o sì fi òfin mi sinu ọkàn rẹ.

2. Pa òfin mi mọ́, kí o lè yè,pa ẹ̀kọ́ mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹyin ojú rẹ,

3. wé wọn mọ́ ìka rẹ,kí o sì kọ wọ́n sí oókan àyà rẹ.

4. Sọ fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arabinrin mi,”kí o sì pe ìmọ̀ ní ọ̀rẹ́ kòríkòsùn rẹ,

5. kí wọ́n baà lè pa ọ́ mọ́,kúrò lọ́dọ̀ alágbèrè obinrin,ati kúrò lọ́wọ́ onírìnkurìn pẹlu ọ̀rọ̀ dídùn rẹ̀.

6. Mo yọjú wo ìta,láti ojú fèrèsé ilé mi.

Ìwé Òwe 7