Ìwé Òwe 28:15-21 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Ọba burúkú tí ó jọba lórí àwọn talaka,dàbí kinniun tí ń bú ramúramù,tabi ẹranko beari tí inú ń bí.

16. Ìkà, aninilára ni olórí tí kò ní òye,ṣugbọn ẹ̀mí ẹni tí ó bá kórìíra à ń jèrè lọ́nà èrú yóo gùn.

17. Bí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan bá ń da eniyan láàmú,yóo di ìsáǹsá ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀,kí ẹnikẹ́ni má ṣe ràn án lọ́wọ́.

18. Ẹni tí ń rìn pẹlu òtítọ́ inú yóo rí ìgbàlà,ṣugbọn ẹni tí ń rìn ségesège yóo ṣubú sinu kòtò.

19. Ẹni tí ń ṣiṣẹ́ oko dáradára, yóo ní oúnjẹ pupọ,ṣugbọn ẹni tí ń fi àkókò rẹ̀ ṣòfò yóo di talaka.

20. Olóòótọ́ yóo ní ibukun lọpọlọpọ,ṣugbọn ẹni tí ń kánjú àtilówó, kò ní lọ láìjìyà.

21. Ojuṣaaju kò dára,sibẹ oúnjẹ lè mú kí eniyan ṣe ohun tí kò tọ́.

Ìwé Òwe 28