Ìwé Òwe 25:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Àwọn òwe mìíràn tí Solomoni pa,tí àwọn òṣìṣẹ́ Hesekaya ọba Juda kọ sílẹ̀ nìwọ̀nyí.

2. Ògo ni ó jẹ́ fún Ọlọrun láti fi nǹkan pamọ́,ṣugbọn ògo ló sá tún jẹ́ fún ọbaláti wádìí nǹkan ní àwárí.

3. Bí ọ̀run ti ga, tí ilẹ̀ sì jìn,bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò lè mọ ohun tí ó wà lọ́kàn àwọn ọba.

4. Yọ́ gbogbo ìdọ̀tí tí ó wà lára fadaka kúrò,alágbẹ̀dẹ yóo sì rí fadaka fi ṣe ohun èlò.

5. Mú àwọn olùdámọ̀ràn ibi kúrò lọ́dọ̀ ọba,a óo sì fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ pẹlu òdodo.

Ìwé Òwe 25